Wo bí ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ NLC ṣe fìpá já lẹ̀kùn ilé aṣòfin àpapọ̀ Nàìjíríà lásìkò ìwọ́de

Awọn ẹgbẹ oṣiṣẹ to n ṣe iwọde ni olu ilu Naijiria, Abuja ti fi ipa ja ilẹkun wọle si ile igbimọ aṣofin apapọ Naijiria to wa nilu Abuja.

Awọn oṣiṣẹ n ṣewọde lori bi gbogbo nnkan ṣe wọngogo lorilẹede Naijiria latari awọn igbesẹ atunto ọrọ aje ti ijọba to wa lode bayii lorilẹede Naijiria n gbe, paapaajulọ yiyọ owo iranwọ ‘subsidy’ ori epo.