Ilé àṣofin ké sí Ààrẹ Buhari láti kéde àwọn agbébọn gẹ́gẹ́ bí jàǹdùkù afẹ̀miṣòfò

Ile asofin Naijiria

Oríṣun àwòrán, others

Ile aṣofin agba ni Naijiria ti ke si Aarẹ Muhammadu Buhari pe ko kede awọn janduku agbebọn gẹgẹ bi agbesunmọmi ni kiakia.

Nibi ijoko ile to waye ni Ọjọru ni awọn sẹnetọ naa ti sọ ọrọ yii.

Bakan naa ni awọn aṣofin sọ pe ko tun kede gbogbo olori awọn agbebọn naa ti ijọba mọ gẹgẹ bi ẹni ti wọn n wa, ko si tọpinpin ibi ti wọn wa lati fi ofin mu wọn fun igbẹjọ.

Wọn tun sọ pe ki Aarẹ Buhari paṣẹ pe ki awọn ọmọ ogun ju ado oloro si ibuba awọn agbebọn naa.

Ijiroro ọhun waye lẹyin ti aṣofin kan lati ipinlẹ Sokoto, Ibrahim Gobir gbe aba kan kalẹ lori eto abo.

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ

Eyi waye lẹyin ọjọ kan ti awọn agbebọn pa eeyan to to ogún, ti wọn si tun ji awọn kan gba lọ ni abule Gatawa, nijọba ibilẹ Sabon Birni nipinlẹ Sokoto.

Bakan naa, awn wọnyii o ṣẹṣẹ maa da ẹmi awọn eeyan Naijiria legbodo paapaa lapa Ariwa.

Ṣaaju ni ikọlu kan ti waye ni abule Gangara, nijọba ibilẹ kan naa.

Ninu ọrọ to sọ, Aarẹ ile aṣofin, Sẹnetọ Ahmad Lawan pe fun fifi kun owo ti ijọba n na sori iṣẹ awọn ọmọ ologun.

O si sọ pe o ti di dandan fun awọn igbimọ nile aṣofin to wa fun eto aabo, lati ri i daju pe wọn n na owo awọn ileeṣẹ ologun fun nkan to yẹ.