Ìjọba àpapọ̀ fún Amẹ́ríkà láṣẹ láti gbé Abba Kyari fún ìgbẹ́jọ́

Abba kyari

Oríṣun àwòrán, Others

Ìjọba Nàìjíríà ti buwọ́lu ìbéèrè orílẹ̀ èdè Amẹ́ríkà láti fi ọ̀gá ọlọ́pàá Abba Kyari ráńṣẹ́ sí orílẹ̀ èdè náà láti lọ kojú ìgbẹ́jọ́ ẹ̀sùn ìwà àjẹbánu tí wọ́n fi kàn án.

Amẹ́ríkà ló ti ṣaájú bèrè fún àṣẹ ìjọba àpapọ̀ láti fi Abba kyari ráńṣẹ́ kò lé kojú ìgbẹ́jọ́ lórí ẹ̀sùn jíjí owó mílíọ̀nù lé ọwọ́ kan dọ́là lórí ẹ̀rọ ayélujára.

Kyari ni orílẹ̀ èdè Amẹ́ríkà fẹ̀sùn kàn pé ó lẹ̀dí àpòpọ̀ pẹ̀lú Ramon Abass tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ mọ̀ sí Hushpuppi àti àwọn mẹ́rin mìíràń láti jí owó náà kó.

Mínísítà fétò ìdájọ́ àti Agbẹjọ́rò àgbà orílẹ̀ èdè yìí, Abubakar Malami lo fi ọ̀rọ̀ yìí léde nínú ẹjọ́ kan tó pè síwájú adájọ́ àgbà ilé ẹjọ́ gíga ìlú Abuja.

Kí ló ti ṣẹlẹ̀ sẹ́yìn?

Malami ni ẹjọ́ náà jẹ́ pípè ní ìdáhùn sí ìbéèrè aṣojú ilẹ̀ Amẹ́ríkà sí Nàìjíríà láti gba orílẹ̀ èdè náà láàyè láti ṣe ìgbẹ́jọ́ Abba Kyari.

Òṣìṣẹ́ àjọ aṣèwádìí ilẹ̀ Amẹ́ríkà, Andrew Innocenti ti fẹ̀sùn kan pé Hushpuppi gbéṣẹ́ fún Kyari lẹ́yìn ti ẹni kan, Chibuzo Vincent dúnkokò láti tú àṣírí èrú owó mílíọ̀nù lé ọwọ́ kan dọ́là owó oníṣòwò kan tó jẹ́ ará ilẹ̀ Qatar.

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ

Innocenti ní òun ní àwọn ẹ̀rí tó fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé Abba Kyari gba owó mílíọ̀nù mẹ́jọ náírà lọ́wọ́ Hushpuppi láti fi nawọ́ gán àti jíju Vincent sí àhámọ́.

Láti inú oṣù kẹrin ọdún tó kọjá ni ilẹ̀ Amẹ́ríkà ti ní kí FBI nawọ́ gán Kyari.

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kyari jìyàn gbogbo ẹ̀sùn yìí, ilé iṣẹ́ ọlọ́pàá ti ní kó lọ rọ́kún nílé títí wọn yóò fi parí ìwádìí lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀.

Abba Kyari tún ń kojú ẹ̀sùn gbígbé egbògi olóró

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ

Ní nǹkan bí ọ̀sẹ̀ méjì sẹ́yìn ni Abba Kyari tún kó sí wàhálà tuntun mìíràn nígbà tí àjọ NDLEA fẹ̀sùn kàn án pé ó lọ́wọ́ nínú bí egbògi olóró ṣe wọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti orílẹ̀ èdè Brazil.

Lọ́sẹ̀ tó kọjá, ilé ẹjọ́ kan dá ẹjọ́ pé kí NDLEA fi sí àhámọ́ fún ọjọ́ mẹ́rìnlá.

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ