CBN kéde afìkún àsìkò tí owó àtijọ́ yóò kúró nílẹ̀

Owo Naira tuntun

Oríṣun àwòrán, @CBN

Gomina Banki Naijiria, Godwin Emefiele ti kede pe ijoba ti fi kun gbendeke asiko ti won yoo ko owo atijo kuro nile.

Emefiele ṣalaye pe lẹyin ọpọlọpọ ipade pẹlu Aarẹ Muhammadu Buhari ni wọn pinnu lati fi kun iye ọjọ ti wọn yoo ko owo naa kuro nilẹ.

Saaju ni wọn ti kede ọjọ kọkanlelọgbọn, oṣu kinni, ọdun 2023 gẹgẹ bi ọjọ to gbẹyin ṣugbọn bayii, wọn ti sun un siwaju di ọjọ kẹwaa, oṣu keji, ọdun 2023.

Emefiele dupẹ lọwọ Buhari fun atilẹyin to sẹ fun un lasiko to n gbe igbesẹ akọni yii .

Emefiele tun salaye pe o ti to ida 75% ninu ọgọrun un owo atijọ to ti wọle bayii

Ati pe oun gbe igbesẹ naa ki odiwon iye nkan ti owo naira le ra ati agbara rẹ le gbe pẹẹli sii ni.

O ni yoo tun dena agbara owo ti awon ajinigbe n gba bii owo itusilẹ ni eyi ti yoo ran awon oṣiṣẹ alaabo lọwọ lati maa ri wọn mu lasiko.

Ojọ kẹwaa, oṣu keji ọdun yii ni wọn ko ni le maa na owo atijọ mọ nigboro Naijiria.

Emefiele sọ pe awọn ti ri 1.9 tirillion ninu 2.7 trillion to ha sita gba wọle pada ni Naijiria bayii.

Emefiele sọ pe to ba tun ti di ọjọ kẹwaa, oṣu keji si ọjọ kẹtadinlogun, oṣu keji, ọdun 2023 yii ni awọn eeyan ṣi ni oore ọfẹ lati paarọ owo atijọ wọn si tuntun ni banki Naijiria apapọ ti a mọ si Central Bank of Nigeria.

Ọṣe kan ni CBN tun ya kalẹ lati ṣe paṣipaarọ owo naa titi yoo fi kasẹ nilẹ tan leyin asiko gbendeke tuntun yii