Gbọ́, Wo àṣírí àgbára aláàfin Adeyemi tó ṣe bí ìbejì àti ìbẹta, Duration 1,57

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ

Alaafin Adeyemi: Ọmọ aláàfin sọ̀rọ̀ lórí àṣírí agbára bàbá rẹ̀ bí Kábíyèsí ṣe bí ìbejì ní ẹ̀ẹ̀mẹta láàrin oṣù mẹ́jọ

Aláàfin ìlú Ọyọ, Ọba Lamidi Ọlayiwọla Adeyẹmi Kẹta tún ti bí ìbejì mi i.

Ìgbà kẹta nìyíì ti yóò bí ìbejì l’ọ́dún 2018 nìkan ṣoṣo.

Bákan nàá ló ti bí ìbẹta rí.

Ọ̀kan lára àwọn olorì rẹ̀, Anuoluwapọ Adeyẹmi ló tún bí ìbejì ọkùnrin kan àti obìnrin láìpẹ́ yìí, èyí tó sọ ọ́ di ìkẹta láàrin oṣù mẹ́jọ.

Iyawo alaafin

Oríṣun àwòrán, @queenomohone/Instgram

Àwọn olorì méjì kan ti bi ìbejì l’ọ́dún 2018.

Bákan nàá ni Olorì Memunat Omowumi Adeyẹmi tóbákan nàá.

Olori Olaitan

Oríṣun àwòrán, @queenola2/Instagram

Amin iyasọtọ kan

Njẹ ki wa ni asiri agbara Alaafin, ẹni to ti le ni ọgọrin ọdun, to fi nbi ibeji ati ibẹta ni ọpọ igba?

Èyí ni ìbéèrè tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ Yorùbá n bèérè.

Ọmọọbabinrin Alaafin, Olubunmi Labiyi bá BBC Yoruba sọ̀rọ̀ nínú fọ́nrán tó wà l’ókè.