EFCC yóò fi ojú Yahaya Bello ba ilé-ẹjọ́ lónìí lórí ẹ̀sùn lílu owó ìlú ní póńpó

Aworan EFCC ati Yahaya Bello

Oríṣun àwòrán, EFCC ati Yahaya Bello/Others

Ajọ to n gbogun ti iwa jibiti ati ajẹbanu lorileede yii, Economic and Financial Crimes Commission, EFCC ti sọ pe awọn yoo fi oju gomina ana nipinlẹ Kogi, Yahaya Adoza Bello ba ile-ẹjọ lonii.

Oni ọjọ kejidinlogun, oṣu kẹrin, ọdun 2024 lori ẹsun ṣiṣe owo to le diẹ ni ọgọrin biliọnu owo naira mọkumọku.

EFCC lo fi eyi lede lopo ayelujara ti Instagram wọn l’Ọjọru, ọsẹ yii, ti wọn si ni ile-ẹjọ giga apapọ to wa niluu Abuja l’awọn yoo fi oju rẹ ba.

Eyi ko ṣai waye pẹlu bi ajọ EFCC ṣe sọ pe awọn gba aṣẹ ile-ẹjọ lati fi ofin gbe Yahaya Bello l’Ọjọru, ọjọ kẹtadinlogun, oṣukẹrin, ọdun 2024.

Bakan naa ni ajọ EFCC tun jẹ ko di mimọ pe iwaju Onidajọ Emeka Nwite ni Yahaya Bello ati awọn mẹrin miran ti wọn fẹsun kan yoo ti kawọ pọyin rojọ.

Awọn mẹta naa ni Alli Bello, Dauda Suleiman ati Abdulsalam Hudu.

Ẹsun mọkandinlogun ọtọọtọ to nii ṣe pẹlu ṣiṣe owo ilu to le diẹ ni ọgọrin biliọnu (N80, 246, 470, 088.88) mọkumọku.

Skip Instagram post

Allow Instagram content?

This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose ‘accept and continue’.

Warning: The BBC is not responsible for the content of external sites.

End of Instagram post

Content is not available

View content on InstagramBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.