Ọkùnrin kan dágbére fáyé lẹ́yìn ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀

Yorùbá ni òwò tí àdá mọ̀-ọ́n-ṣe ní ń kán àdá léyín, àti pé ikún ń jọ̀gẹ̀dẹ̀ ó ń rèdí kò mọ̀ pé ohun tó dùn a máa pani.

Ọkùnrin kan tí wọn kò tíì mọ orúkọ àti ọ̀nà rẹ̀ kan ti fò ṣánlẹ̀, tó sì gba èkuru lọ́wọ́ ẹbọra ní ilé ìtura kan ní Ada George, ìjọba ìbílẹ̀ Obio-Akpor, ìpínlẹ̀ Rivers lẹ́yìn tó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin kan.

Ẹnìkan tí òun náà wà ní ilé ìtura yìí ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ kí a dárúkọ òun ṣàlàyé fún àwọn akọ̀ròyìn pé ní nǹkan bí ago méjì òru ni obìnrin yìí lọ gbá ilẹ̀kùn yàrá àlejò mìíràn láti ké gbàǹjerè pé ẹni tí àwọn jọ wọ yàrá ti ṣubú lulẹ̀.

Nígbà tí àwọn akọròyìn kàn sí agbẹnusọ àjọ ìpínlẹ̀ Rivers, Grace Iringe-Kokom jẹ́rìí sí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.Iringe-Kokom ní àwọn ti fi obìnrin náà àti alákòso ilé ìtura sí àhámọ́ àti pé ìwádìí ti bẹ̀rẹ̀ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.