Ọ̀pọ̀ ajìjàgbara Odua Nation pẹ̀lú ohun ìjà olóró ya wọ ọgbà ọ́fìsì Gómìnà Oyo

Aworan

Oríṣun àwòrán, Others

Ni owurọ ọjọ Satide ni awọn eeyan kan ti wọn furasi si pe wọn jẹ ọmọ lẹyin ẹgbẹ ajijagbara Odua Nation yawọ ninu ọgba ọfisi Gomina Oyo to wa niluu Ibadan to jẹ olu ilu ipinlẹ naa.

Iroyin to tẹ Ileeṣẹ BBC Yoruba lọwọ ni pe awọn ajijagbara naa yawọ ile igbimọ aṣofin Oyo, ti wọn si parọ asia orilẹede Naijiria pẹlu ti Odua Nation ki awọn ọmọ ologun to de si ibẹ.

Ninu fọnran to tẹ wa lọwọ, awọn ajijagbara naa ni wọn wọ aṣọ ologun lasiko ti ọwọ tẹ wọn.

Bakan naa ni fọnran ọhun tun safihan bi ọwọ Ileeṣẹ Ọlọpaa ṣe tẹ wọn, ti wọn si da wọn dubulẹ ninu ọgba naa

Nigba to n fi iroyin naa mulẹ, oludanmọran si Gomina lori eto abo nipinlẹ Oyo, Fatia Owoseni Rtd ni ọwọ ti tẹ afurasi mẹrindinlogun lara awọn afurasi naa.

Bakan Oludamọran si Gomina lori iroyin, Abosede Sodiq naa fidi isẹlẹ naa mulẹ, o ni bi wọn se yawọ ninu ọgba ọfisi Gomina ni wọn si bẹrẹ si ni yin ibọn soke.

O ni ọwọ awọn agbofinro ti tẹ pupọ awọn afurasi naa

“A ti ke si awọn araalu nitori awọn eeyan yii ni wọn mura ninu aṣọ ologun, pe ki wọn fura si iru awọn eeyan bẹ.”

Nibayii, ọpọ awọn ẹsọ alabo, lati ori Ileeṣẹ ọlọpaa, ileeṣẹ ologun ati awọn Amọtẹkun lo ti wa kaakiri agbegbe naa lati ri pe alaafia jọba.

Bakan naa ni wọn ti gbe igi dina awọn pju ọna kan, ti wọn si rọ awọn araalu lati ma gba agbegbe ti wọn gbe igi dana.