EFCC ló láṣẹ lábẹ́ òfin láti ṣe ẹjọ́ Emefiele, kìí ṣe DSS – Falana

Emefiele

Oríṣun àwòrán, @NTANewsNow

Agbẹjọro agba Naijiria, Femi Falana, ti sọ pe ko tọ si ileeṣẹ ọtẹlẹmuyẹ Naijiria, DSS, lati pe gomina CBN ti wọn rọ loye, Godwin Emefiele, lẹjọ.

Falana ninu atẹjade kan sọ pe o yẹ ki wọn tare Emefiele si ikawọ ajọ to n gbogun ti iwa ajẹbanu, EFCC, ni kankan.

Gẹgẹ bii ohun to sọ, EFCC lo laṣẹ labẹ ofin lati ṣe ẹjọ emefiel, kii ṣe DSS.

O ni “Ni nkan bii oṣu diẹ sẹyin, ileeṣẹ SSS fi ẹsun ṣiṣẹ onigbọwọ awọn agbesumọmi atawọn ẹsun mi kan Godwin Emefiele….”

“Lasiko naa, ijọba Buhari dena akitiyan SSS lati fi ṣikun ofun mu Emefiele ati lati ṣe ẹjọ rẹ.”

“Amọ lẹyin ti Aarẹ Bola Tinubu ni ko lọ rọọkun nile, SSS na ọwọ gan niluu Eko, wọn si gbe lọ si Abuja.”

Bo tilẹ jẹ pe DSS kọkọ sọ pe Emefiele ko si lakata awọn, wọn pada sọrọ soke pe awọn ti fi ṣikun ofin mu afurasi naa.

Ẹwẹ, Falana ni awọn idajọ kan to ti waye sẹyin ni irufẹ ẹjọ bayii fi han pe ko tọ si DSS lati ṣe ẹjọ afurasi ọhun, bi komṣe EFCC.

O ṣalaye pe ninu igbẹjọ Bukola Saraki ati ijọba apapọ to waye lọdun 2018, idajọ ile ẹjọ to ga julọ ni Naijiria lọdun naa lọhun fi han gbangba ikọja aye ni DSS n ṣe bo ṣe mu Emefiele.

O pari ọrọ rẹ pe “Ni ilana idajọ ile ẹjọ to ga julọ ninu ẹjọ Saraki, SSS ko laṣẹ lati ṣe iwadii tabi ṣe ẹjọ Emefiele lori ọrọ to jẹ mọ ṣiṣẹ owo baṣubaṣu atawọn ẹsun mii to ni ṣe pẹlu ọrọ aje ilu.”