ASUU Strike: ìjọba àpapọ̀ àti ẹgbẹ́ àwọn olùkọ́ yóò ṣèpàdé lónìí

Ìjọba àpapọ̀ àti ẹgbẹ́ ASUU ń ṣèpàdé

Oríṣun àwòrán, others

Ijoba Naijiria ati egbẹ́ awọn Oluko Fasiti yoo se ipade loni lori ọ̀rọ̀ iyanselodi wọ́n

Lónìí, ọjọ́ kìíní, oṣù kẹta, ọdún 2022 ni ìjọba àpapọ̀ àti ẹgbẹ́ àwọn olùkọ́ ni orílẹ̀ èdè Nàìjíríà, ASUU yóò tún ṣèpàdé láti jíròrò láti wá ojútùú sí ìfaǹfà tó ń wáyé láàárín àwọn méjéèjì lórí ìyanṣẹ́lódì tí ASUU gùnlé.

Ìpàdé tòní ni ó jẹ́ ìtẹ̀síwájú lórí gbogbo àwọn ìfẹnùkò wọn níbi ìpàdé tí wọ́n ṣe lọ́sẹ̀ tó kọjá.

Ààrẹ ẹgbẹ́ ASUU, Ọ̀jọ̀gbọ́n Emmanuel Osodeke ní òun gba ìpè ìjọba àpapọ̀ lánàá láti tún pàdé fún ìjíròrò lónìí.

Osodeke ní òun kò rò wí pé àwọn ń tẹ̀síwájú bó ṣe jẹ́ pé gbogbo ìjíròrò àwọn kò ì tíì so èso rere láti ìgbà tí àwọn ti gùnlé ìyanṣẹ́lódì.

Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ lórí ọ̀rọ̀ tí Mínísítà fọ́rọ̀ òṣìṣẹ́, Chris Ngige sọ wí pé ìjọba ò le ṣe ẹ̀kúnwó owó olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ fásitì lásìkò yìí, Osodeke ní ìjọba àpapọ̀ kò ṣe òótọ́ pẹ̀lú àwọn.

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ

Ó ní bí Ààrẹ bá le buwọ́lu ẹ̀kúnwó àwọn ọlọ́pàá àti ti àwọn olùkọ́ ilé ẹ̀kọ́ alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ àti girama, tí àlékún tún bá owó ìrìnà àwọn ìjọba kò sí ohun tó ní kí ìjọba má lè ṣe àlékún owó oṣù àwọn náà.

Bákan náà ló fi ìkọnilóminú hàn pé ìjọba kò buwọ́lu àbá owó oṣù wọn tuntun.

Àwọn àmúyẹ fun gbígbọ́ orin ko le ṣiṣẹ lori ẹ̀rọ rẹ

Wo iye igba ti ASUU ti da ise sile ni Naijiria:

BBC se akojopo odiwon iye igba ti egbe Oluko Fasiti ASUU ti se iyanselodi pe:

ASUU
ASUU