A fara mọ́ lílo owó Naira tuntun tí CBN ṣe – Ìgbìmọ̀ májẹ̀kóbàjẹ́ Nàíjíríà

Naira atijọ ati tuntun

Oríṣun àwòrán, CBN

Awọn ọmọ Naijiria ni ko tii mọ odo ti wọn yoo da ọrunla si nidi lilo owo naira, boya ki wọn maa na Naira tuntun lọ ni tabi ti atijọ tabi maa na mejeeji papọ.

Idarudapọ naa si lo n waye nitori bi ile ẹjọ to ga julọ nilẹ wa se wọgile gbedeke ọjọ Kẹwa osu keji ti CBN fi lelẹ fun lilo Naira atijọ.

Kete ti idajọ naa waye, si ni ijọba apapọ ti morile ile ẹjọ to ga julọ pada pe ko wọgile ẹjọ kan tawọn gomina APC pe, eyi to n tako atunse Naira naa.

Ni bayii ti gbedeke ti CBN fi lelẹ naa pari lọjọ Ẹti ana, banki apapọ ilẹ wa, CBN ati ijọba apapọ ko ti kede pato ohun ti yoo sẹlẹ, si irufẹ owo Naira ta maa lo.

Amọ ọmọ Naijiria ko si ti mọ boya ki wọn maa na owo Naira atijọ lọ ni tabi tuntun nikan ni ki wọn maa lo tabi mejeeji.

Awọn ọmọ Naijiria ni ileepo atawọn ibudo itaja ko gba Naira atijọ mọ

Ọpọ awọn ọmọ Naijiria si lo ti n kọminu lori isẹlẹ yii nitori ko ye wọn mọ.

Koda, ọpọ Banki olokoowo lo n fi iwe ransẹ sawọn onibara wọn pe gbedeke ti CBN fi lelẹ fawọn ti kọja, owo tuntun lo ku tawọn yoo maa lo.

Meeli tawọn banki kan fi ransẹ sawọn onibara rẹ lori gbedeke naa lọjọbọ ati lọjọ Ẹti fihan pe gbedeke CBN naa n fidi mulẹ.

Ọpọ awọn eeyan to si ba BBC sọrọ lori isẹlẹ yii lo n gbara ta pe awọn ileepo atawọn ibudo itaja kan ti n fariga lati maa gba Naira atijọ lọwọ awọn.

Alaye wọn ni pe wọn ti pasẹ fawọn lati ye lo owo naa mọ

Ijọba ni oun yoo tẹle asẹ ile ẹjọ to fi wọgile gbedeke ọjọ ti lilo Naira atijọ mọ amọ awọn eeyan kan si n kọ owo atijọ

Bakan naa lo tun kede pe oun yoo tẹle asẹ ile ẹjọ naa eyi to fi wọgile gbedeke ọjọ ti lilo Naira atijọ mọ.

Sugbọn o se ni laanu pe ọpọ ọmọ Naijiria ni ko tẹle ikede ijọba naa.

Minisita feto idajọ, Abubakar Malami,sọ fun BBC pe nitori asẹ ile ẹjọ naa lori ẹjọ tawọn gomina APC pe, oun gba ki wọn maa na owo atijọ lọ

O ni “Ijọba ni ẹtọ lati ba ile ẹjọ sọrọ, ko le se alaye lẹkunrẹrẹ nipa ohun ta mọ lori igbesẹ CBN naa,.

Eleyi yoo si ran ileẹjọ lọwọ nidi idajọ ti yoo gbe kalẹ lori ọrọ yii.”

O wa yan pe niwọn igba ti ile ẹjọ ti gbe asẹ kalẹ nidi lilo Naira atijọ, ẹtọ ijọba ni lati tẹle asẹ naa.

Ipinnu yii si lo waye lasiko yii ti igbimọ majẹkobajẹ nilẹ wa rọ banki CBN lati pese owo tuntun ti yoo to ọmọ Naijiria na tabi ko da owo atijọ to ti gba sita fun nina.

Igbimọ majẹkobajẹ naa ni eyi nikan ni ọna abayọ si isoro ilẹ yii nitori isoro nla lawọn araalu n koju nidi riri owo na.

Ijọba apapọ fẹ ro awijare tiẹ lori idi ti atunse Naira fi gbọdọ waye

Ironu nla si lo bawọn ọmọ Naijiria to ba BBC sọrọ, wọn ni nigba tawọn eeyan ko gba owo atijọ mọ lọwọ awọn, ko si owo tuntun rara nilẹ ti awọn fẹ na.

Ọpọ olokoowo ti ọrọ yii kan, si lo n fi ika hanu fun wa pe akoa nla nla ni igbesẹ yii ti da si awn lọrun nidi okoowo awọn.

Koda, awọn eeyan to n ta eroja oun tẹnu n jẹ eyi to le tete bajẹ, bii ata, eso atawọn eroja miran lo n bu sẹkun nitori aita ọja, ti eroja wn si n bajẹ mọ wọn lọwọ.

Idarudapọ nla si lo n ba awọn ọmọ Naijiria lori boya ki wọn maa na owo atijọ abi tuntun

Nibayii, ijọba apapọ ti setan lati ro awijare tiẹ nigba ti igbẹjọ ba bẹrẹ nile ẹjọ to ga julọ lori idi ti atunse Naira fi gbọdọ duro ati idi ti gbedeke lilo naira atijọ mọ fi gbọdọ waye.